Ìwé Òwe 19:14-21 BIBELI MIMỌ (BM)

14. A máa ń jogún ilé ati ọrọ̀ lọ́wọ́ baba ẹni,ṣugbọn OLUWA níí fúnni ní aya rere.

15. Ìwà ọ̀lẹ a máa múni sùn fọnfọn,ebi níí sìí pa alápá-má-ṣiṣẹ́.

16. Ẹni tí ó bá pa òfin mọ́, ẹ̀mí ara rẹ̀ ni ó pamọ́,ẹni tí ó kọ ọ̀nà Ọlọrun sílẹ̀ yóo kú.

17. Ẹni tí ó ṣe ojurere fún àwọn talaka, OLUWA ni ó ṣe é fún,OLUWA yóo sì san ẹ̀san rẹ̀ fún un.

18. Bá ọmọ rẹ wí nígbà tí ó sì lè gbọ́ ìbáwí,má sì ṣe wá ìparun rẹ̀.

19. Onínúfùfù yóo jìyà inúfùfù rẹ̀,bí o bá gbà á sílẹ̀ lónìí, o níláti tún gbà á sílẹ̀ lọ́la.

20. Gbọ́ ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́,kí o lè rí ọgbọ́n lò lẹ́yìn ọ̀la.

21. Ọpọlọpọ ni èrò tí ó wà lọ́kàn ọmọ eniyan,ṣugbọn ìfẹ́ OLUWA ni àṣẹ.

Ìwé Òwe 19