Ìwé Òwe 17:14-20 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Ìbẹ̀rẹ̀ ìjà dàbí kí eniyan ya odò tí wọn sé,dá a dúró kí ó tó di ńlá.

15. Ẹni tí ń gbé àre fún ẹlẹ́biati ẹni tí ń gbé ẹ̀bi fún aláre,OLUWA kórìíra ekinni-keji wọn.

16. Owó kò wúlò lọ́wọ́ òmùgọ̀ pé kí ó fi ra ọgbọ́n,nígbà tí kò ní òye?

17. Ọ̀rẹ́ a máa fẹ́ni nígbà gbogbo,ṣugbọn a bí arakunrin láti dúró tini ní ìgbà ìpọ́njú.

18. Ẹni tí kò bá gbọ́n níí jẹ́jẹ̀ẹ́,láti ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ̀.

19. Ẹni tí ó bá fẹ́ràn ìjà fẹ́ràn ẹ̀ṣẹ̀,ẹni tí ó bá fẹ́ràn kí á máa fi owó ṣe àṣehàn ń wá ìparun.

20. Ẹni tí ó ní ọkàn ẹ̀tàn kò ní ṣe àṣeyege,ẹlẹ́nu meji yóo bọ́ sinu ìyọnu.

Ìwé Òwe 17