Ìwé Òwe 16:4-15 BIBELI MIMỌ (BM)

4. OLUWA a máa jẹ́ kí ohun gbogbo yọrí sí bí ó bá ti fẹ́,ó dá eniyan burúkú fún ọjọ́ ìyọnu.

5. OLUWA kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ agbéraga,dájúdájú kò ní lọ láìjìyà.

6. Àánú ati òtítọ́ a máa ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀,ìbẹ̀rù OLUWA a sì máa mú ibi kúrò.

7. Bí ọ̀nà eniyan bá tẹ́ OLUWA lọ́rùn,a máa mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ pàápàá bá a gbé pẹlu alaafia.

8. Ìwọ̀nba ọrọ̀ pẹlu òdodo,sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ tí a kójọ lọ́nà èrú lọ.

9. Eniyan lè jókòó kí ó ṣètò ìgbésẹ̀ rẹ̀,ṣugbọn OLUWA níí tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni.

10. Pẹlu ìmísí Ọlọrun ni ọba fi ń sọ̀rọ̀,ìdájọ́ aiṣododo kò gbọdọ̀ ti ẹnu rẹ̀ jáde.

11. Ti OLUWA ni òṣùnwọ̀n pípé,iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo ohun tí à ń wọ̀n.

12. Àwọn ọba kórìíra ibi ṣíṣe,nítorí nípa òdodo ni a fìdí ìjọba múlẹ̀.

13. Inú ọba a máa dùn sí olódodo,ọba sì máa ń fẹ́ràn àwọn tí ń sọ òtítọ́.

14. Iranṣẹ ikú ni ibinu ọba,ọlọ́gbọ́n eniyan níí tù ú lójú.

15. Ìyè wà ninu ojurere ọba,ojurere rẹ̀ sì dàbí ṣíṣú òjò ní àkókò òjò àkọ́rọ̀.

Ìwé Òwe 16