Ìwé Òwe 16:22-28 BIBELI MIMỌ (BM)

22. Orísun ìyè ni ọgbọ́n jẹ́ fún àwọn tí wọn ní i,agọ̀ sì jẹ́ ìjìyà fún àwọn òmùgọ̀.

23. Ọgbọ́n inú níí mú kí ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n tọ̀nà,ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ a sì máa yíni lọ́kàn pada.

24. Ọ̀rọ̀ tí ó tuni lára dàbí afárá oyin,a máa mú inú ẹni dùn, a sì máa mú ara ẹni yá.

25. Ọ̀nà kan wà tí ó tọ́ lójú eniyan,ṣugbọn òpin rẹ̀, ikú ni.

26. Ebi níí mú kí òṣìṣẹ́ múra síṣẹ́,ohun tí a óo jẹ ní ń lé ni kiri.

27. Eniyan lásán a máa pète ibi,ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ dàbí iná tí ń jóni.

28. Ṣòkèṣodò a máa dá ìjà sílẹ̀,ọ̀rọ̀ àhesọ a máa tú ọ̀rẹ́ kòríkòsùn.

Ìwé Òwe 16