Ìwé Òwe 14:23-27 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Kò sí iṣẹ́ kan tí kò lérè,ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹnu lásán láìsí iṣẹ́, a máa sọ eniyan di aláìní.

24. Ọgbọ́n ni adé àwọn ọlọ́gbọ́n,ṣugbọn ìwà aláìgbọ́n jẹ́ yẹ̀yẹ́ àwọn òmùgọ̀.

25. Ẹlẹ́rìí tòótọ́ a máa gba ẹ̀mí là,ṣugbọn ọ̀dàlẹ̀ ni òpùrọ́.

26. Ninu ìbẹ̀rù OLUWA ni igbẹkẹle tí ó dájú wà,níbẹ̀ ni ààbò wà fún àwọn ọmọ ẹni.

27. Ìbẹ̀rù OLUWA ni orísun ìyè,òun níí mú ká yẹra fún tàkúté ikú.

Ìwé Òwe 14