Ìwé Òwe 13:19-25 BIBELI MIMỌ (BM)

19. Bí èrò ọkàn ẹni bá ṣẹ, a máa fúnni láyọ̀,ṣugbọn àwọn òmùgọ̀ kórìíra ati kọ ibi sílẹ̀.

20. Bí eniyan bá ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóo gbọ́n,ṣugbọn ẹni tí ó bá ń bá òmùgọ̀ kẹ́gbẹ́ yóo ṣìnà.

21. Àjálù kì í dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,ṣugbọn olódodo yóo máa rí ire.

22. Eniyan rere a máa fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀,ṣugbọn àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ń kó ọrọ̀ jọ fún àwọn olóòótọ́.

23. Oko tí talaka dá lè mú ọpọlọpọ oúnjẹ jáde,ṣugbọn àwọn alaiṣootọ níí kó gbogbo rẹ̀ lọ.

24. Ẹni tí kì í bá na ọmọ rẹ̀ kò fẹ́ràn rẹ̀,ṣugbọn ẹni tí ó fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ yóo máa bá a wí.

25. Olódodo a máa jẹ àjẹtẹ́rùn,ṣugbọn eniyan burúkú kì í yó.

Ìwé Òwe 13