Ìwé Òwe 12:21-28 BIBELI MIMỌ (BM)

21. Nǹkan burúkú kò ní ṣẹlẹ̀ sí olódodo,ṣugbọn eniyan burúkú yóo kún fún ìyọnu.

22. OLUWA kórìíra ẹni tí ń parọ́,ṣugbọn inú rẹ̀ dùn sí olóòótọ́.

23. Ọlọ́gbọ́n a máa fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́,ṣugbọn àwọn òmùgọ̀ a máa kéde agọ̀ wọn.

24. Ẹni tí ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ ni yóo máa jẹ́ olórí,ṣugbọn ọ̀lẹ ni a óo máa mú ṣiṣẹ́ tipátipá.

25. Ọ̀pọ̀ ìpayà máa ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá eniyan,ṣugbọn ọ̀rọ̀ rere a máa mú inú eniyan dùn.

26. Olódodo a máa yipada kúrò ninu ibi,ṣugbọn ìwà ẹni ibi a máa mú un ṣìnà.

27. Ọwọ́ ọ̀lẹ kò lè tẹ ohun tí ó ń lé,ṣugbọn ẹni tí ń fi tọkàntọkàn ṣiṣẹ́ yóo ní ọpọlọpọ ọrọ̀.

28. Ní ọ̀nà òdodo ni ìyè wà,kò sí ikú ní ojú ọ̀nà rẹ̀.

Ìwé Òwe 12