Ìwé Òwe 10:8-27 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ọlọ́gbọ́n a máa pa òfin mọ́,ṣugbọn òmùgọ̀ onísọkúsọ yóo di ẹni ìparun.

9. Ẹni tí ó bá jẹ́ olóòótọ́ eniyan, yóo máa rìn láìfòyà,ṣugbọn àṣírí alágàbàgebè yóo tú.

10. Ẹni tí bá ń ṣẹ́jú sí ni láti sọ̀rọ̀ èké, a máa dá ìjàngbọ̀n sílẹ̀,ṣugbọn ẹni tí bá ń báni wí ní gbangba, ń wá alaafia.

11. Ẹnu olódodo dàbí orísun omi ìyè,ṣugbọn eniyan burúkú a máa fi ìwà ìkà sinu,a sì máa sọ̀rọ̀ rere jáde lẹ́nu.

12. Ìkórìíra a máa rú ìjà sókè,ṣugbọn ìfẹ́ a máa fojú fo gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ dá.

13. Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n níí máa ń jáde lẹ́nu ẹni tí ó ní òye,ṣugbọn kùmọ̀ ló yẹ ẹ̀yìn ẹni tí kò gbọ́n.

14. Ọlọ́gbọ́n eniyan a máa wá ìmọ̀ kún ìmọ̀,ṣugbọn ọ̀rọ̀ òmùgọ̀ máa ń fa ìparun mọ́ra.

15. Ohun ìní ọlọ́rọ̀ ni ààbò rẹ̀,ṣugbọn àìní talaka ni yóo pa talaka run.

16. Èrè àwọn olódodo a máa fa ìyè,ṣugbọn èrè àwọn eniyan burúkú a máa fà wọ́n sinu ẹ̀ṣẹ̀.

17. Ẹni tí ó bá gba ìtọ́ni wà ní ọ̀nà ìyè,ṣugbọn ẹni tí ó bá kọ ìbáwí yóo ṣìnà.

18. Ẹni tí ó di eniyan sinu jẹ́ ẹlẹ́tàn eniyan,ẹni tí ó bá sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́, òmùgọ̀ ni.

19. Bí ọ̀rọ̀ bá ti pọ̀ jù, àṣìsọ a máa wọ̀ ọ́,ṣugbọn ẹni tí ó bá kó ẹnu ara rẹ̀ ní ìjánu, ọlọ́gbọ́n ni.

20. Ọ̀rọ̀ ẹnu olódodo dàbí fadaka,ṣugbọn èrò ọkàn eniyan burúkú kò já mọ́ nǹkankan.

21. Ọ̀rọ̀ ẹnu olódodo a máa ṣe ọpọlọpọ eniyan ní anfaani,ṣugbọn òmùgọ̀ eniyan a máa kú nítorí àìgbọ́n.

22. Ibukun OLUWA ní ń mú ni í là,kì í sì í fi làálàá kún un.

23. Ibi ṣíṣe a máa dùn mọ́ òmùgọ̀,ṣugbọn ìwà ọgbọ́n ni ayọ̀ fún ẹni tí ó mòye.

24. Ohun tí eniyan burúkú ń bẹ̀rù ni yóo dé bá a,ohun tí olódodo ń fẹ́ ni yóo sì rí gbà.

25. Nígbà tí ìjì líle bá ń jà, a gbá ẹni ibi lọ,ṣugbọn olódodo a fẹsẹ̀ múlẹ̀ títí lae.

26. Bí ọtí kíkan ti rí sí eyín,ati bí èéfín ti rí sí ojú,bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ rí sí ẹni tí ó bẹ̀ ẹ́ níṣẹ́.

27. Ìbẹ̀rù OLUWA a máa mú kí ẹ̀mí eniyan gùn,ṣugbọn ìgbé ayé eniyan burúkú yóo kúrú.

Ìwé Òwe 10