Ìwé Òwe 1:6-20 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Láti lè mọ òwe ati àkàwé ọ̀rọ̀,ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ati àdììtú ọ̀rọ̀.

7. Ìbẹ̀rù OLUWA ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,ṣugbọn àwọn òmùgọ̀ a máa pẹ̀gàn ọgbọ́n ati ẹ̀kọ́.

8. Ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ẹ̀kọ́ baba rẹ,má sì kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ,

9. nítorí pé ẹ̀kọ́ tí wọn bá kọ́ ọ yóo dàbí adé tí ó lẹ́wà lórí rẹ,ati bí ohun ọ̀ṣọ́ ní ọrùn rẹ.

10. Ìwọ ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,o ò gbọdọ̀ gbà.

11. Bí wọn bá wí pé,“Tẹ̀lé wa ká lọ,kí á lọ sápamọ́ láti paniyan,kí á lúgọ de aláìṣẹ̀,

12. jẹ́ kí á gbé wọn mì láàyèkí á gbé wọn mì lódidi bí isà òkú,

13. a óo rí àwọn nǹkan olówó iyebíye kó,ilé wa yóo sì kún fún ìkógun.

14. Ìwọ ṣá darapọ̀ mọ́ wa,kí á sì jọ lẹ̀dí àpò pọ̀.”

15. Ọmọ mi, má bá wọn kẹ́gbẹ́,má sì bá wọn rìn,

16. nítorí ọ̀nà ibi ni ẹsẹ̀ wọn máa ń yá sí,wọ́n a sì máa yára láti paniyan.

17. Asán ni àwọ̀n tí eniyan dẹ sílẹ̀,nígbà tí ẹyẹ tí a dẹ ẹ́ fún ń woni,

18. ṣugbọn ẹ̀jẹ̀ ara wọn ni irú àwọn eniyan bẹ́ẹ̀ lúgọ dè,ìparun ẹ̀mí ara wọn ni wọ́n lúgọ tí wọn ń retí.

19. Bẹ́ẹ̀ ni ti àwọn tí wọ́n ń fi ipá kó ọrọ̀ jọ rí,ọrọ̀ tí wọn fi ipá kójọ níí gba ẹ̀mí wọn.

20. Ọgbọ́n ń kígbe ní òpópónà,ó ń pariwo láàrin ọjà,

Ìwé Òwe 1