Hagai 1:1-3 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ní ọjọ́ kinni, oṣù kẹfa, ọdún keji ìjọba Dariusi, OLUWA rán wolii Hagai sí Serubabeli, ọmọ Ṣealitieli, gomina ilẹ̀ Juda, ati sí Joṣua ọmọ Jehosadaki, olórí alufaa.

2. OLUWA àwọn ọmọ ogun ní: “Àwọn eniyan wọnyi ní, kò tíì tó àkókò láti tún Tẹmpili kọ́.”

3. Nítorí náà ni OLUWA ṣe rán wolii Hagai sí wọn ó ní,

Hagai 1