Ẹkún Jeremaya 3:59-65 BIBELI MIMỌ (BM)

59. O ti rí nǹkan burúkú tí wọ́n ṣe sí mi,OLUWA, dá mi láre.

60. O ti rí gbogbo ìgbẹ̀san wọn,ati gbogbo ète wọn lórí mi.

61. “O ti gbọ́ bí wọn tí ń pẹ̀gàn mi, OLUWA,ati gbogbo ète wọn lórí mi.

62. Gbogbo ọ̀rọ̀ ati èrò àwọn ọ̀tá mi sí mi:ibi ni lojoojumọ.

63. Kíyèsí i, wọn ìbáà jókòó,wọn ìbáà dìde dúró,èmi ni wọ́n máa fi ń kọrin.

64. “O óo san ẹ̀san fún wọn, OLUWA,gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn.

65. Jẹ́ kí ojú inú wọn fọ́,kí ègún rẹ sì wà lórí wọn.

Ẹkún Jeremaya 3