Ẹkisodu 22:18-22 BIBELI MIMỌ (BM)

18. “Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí àjẹ́ wà láàyè.

19. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹranko lòpọ̀, pípa ni kí wọ́n pa á.

20. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá rúbọ sí oriṣa-koriṣa kan lẹ́yìn OLUWA, píparun ni kí wọ́n pa á run.

21. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ pọ́n àlejò lójú tabi kí ó ni ín lára, nítorí pé ẹ̀yin náà ti jẹ́ àlejò rí ní ilẹ̀ Ijipti.

22. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ fìyà jẹ opó tabi aláìníbaba.

Ẹkisodu 22