1. OLUWA sọ fún Mose ati Aaroni ní ilẹ̀ Ijipti pé,
2. “Oṣù yìí ni yóo jẹ́ oṣù kinni ọdún fún yín.
3. Ẹ sọ fún gbogbo ìjọ eniyan Israẹli pé, ní ọjọ́ kẹwaa oṣù yìí, ọkunrin kọ̀ọ̀kan ninu ìdílé kọ̀ọ̀kan yóo mú ọ̀dọ́ aguntan kọ̀ọ̀kan tabi àwọ́nsìn kọ̀ọ̀kan; ọ̀dọ́ aguntan kan fún ilé kan.