Àwọn Ọba Kinni 12:19-23 BIBELI MIMỌ (BM)

19. Láti ìgbà náà ni Israẹli ti ń bá ìdílé Dafidi ṣọ̀tẹ̀ títí di òní yìí.

20. Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé Jeroboamu ti pada dé láti ilẹ̀ Ijipti, wọ́n pè é sí ibi ìpàdé kan tí wọ́n ṣe, wọ́n sì fi jọba Israẹli. Kò sí ẹni tí ó tẹ̀lé ìdílé Dafidi, àfi ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo.

21. Nígbà tí Rehoboamu pada dé Jerusalẹmu, ó ṣa ọ̀kẹ́ mẹsan-an (180,000) ọmọ ogun tí wọ́n jẹ́ akikanju jùlọ láti inú ẹ̀yà Juda ati ti Bẹnjamini, láti lọ gbógun ti ilé Israẹli kí wọ́n sì gba ìjọba ìhà àríwá Israẹli pada fún un.

22. Ṣugbọn Ọlọrun sọ fún wolii Ṣemaaya,

23. pé kí ó jíṣẹ́ fún Rehoboamu, ọba Juda ati gbogbo ẹ̀yà Juda ati ti Bẹnjamini,

Àwọn Ọba Kinni 12