7. Ẹ má jẹ́ kí ó sinmi,títí yóo fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀,títí yóo fi sọ ọ́ di ìlú ìyìn láàrin gbogbo ayé.
8. OLUWA ti fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ búra,ó ti fi agbára rẹ̀ jẹ́ ẹ̀jẹ́,pé òun kò ní fi ọkà oko rẹ,ṣe oúnjẹ fún àwọn ọ̀tá rẹ mọ́;àwọn àjèjì kò sì ní mu ọtí waini rẹ,tí o ṣe wahala lé lórí mọ́.
9. Ṣugbọn àwọn tí ó bá gbin ọkà, ni yóo máa jẹ ẹ́,wọn óo sì máa fìyìn fún OLUWA;àwọn tí ó bá sì kórè àjàrà ni yóo mu ọtí rẹ̀,ninu àgbàlá ilé mímọ́ mi.