6. OLUWA ní nǹkan kékeré ni kí n jẹ́ iranṣẹ òun,láti gbé àwọn ẹ̀yà Jakọbu dìde, ati láti kó àwọn ọmọ Israẹli tí ó kù jọ.Ó ní òun óo fi mí ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn orílẹ̀-èdèkí ìgbàlà òun lè dé òpin ayé.
7. Ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA, Olùràpadà Israẹli, ati Ẹni Mímọ́ rẹ̀, sọ,fún ẹni tí ayé ń gàn,tí àwọn orílẹ̀-èdè kórìíra,iranṣẹ àwọn aláṣẹ,ó ní, “Àwọn ọba yóo rí ọ, wọn óo dìde,àwọn ìjòyè yóo rí ọ, wọn óo sì dọ̀bálẹ̀.Nítorí OLUWA, tí ó jẹ́ olódodo,Ẹni Mímọ́ Israẹli, tí ó ti yàn ọ́.”
8. OLUWA ní,“Ní àkókò ìtẹ́wọ́gbà mo dá ọ lóhùn,lọ́jọ́ ìgbàlà, mo ràn ọ́ lọ́wọ́.Mo ti pa ọ́ mọ́,mo sì ti fi ọ́ dá majẹmu pẹlu àwọn aráyé,láti fìdí ilẹ̀ náà múlẹ̀,láti pín ilẹ̀ tí ó ti di ahoro.
9. Kí o máa sọ fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n pé, ‘Ẹ jáde,’ati fún àwọn tí ó wà ninu òkùnkùn pé, ‘Ẹ farahàn.’Wọn óo rí ohun jíjẹ ní gbogbo ọ̀nà,gbogbo orí òkè yóo sì jẹ́ ibùjẹ fún wọn.