2. OLUWA ní, “N óo lọ ṣáájú rẹ,n óo sọ àwọn òkè ńlá di pẹ̀tẹ́lẹ̀;n óo fọ́ ìlẹ̀kùn idẹ,n óo sì gé ọ̀pá ìlẹ̀kùn irin.
3. N óo fún ọ ní ìṣúra tí wọ́n fi pamọ́ sinu òkùnkùn,ati àwọn nǹkan tí wọ́n kó pamọ́ síkọ̀kọ̀;kí o lè mọ̀ pé èmi, OLUWA, Ọlọrun Israẹli,ni mo pè ọ́ ní orúkọ rẹ.
4. Nítorí Jakọbu, iranṣẹ mi,ati Israẹli, àyànfẹ́ mi,mo pè ọ́ ní orúkọ rẹ.Mo pe orúkọ rẹ ní àpèjá, bẹ́ẹ̀ ni o kò mọ̀ mí.
5. “Èmi ni OLUWA kò sí ẹlòmíràn,kò sí Ọlọrun mìíràn lẹ́yìn mi.Mo dì ọ́ ní àmùrè bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o kò mọ̀ mí.