27. Èmi OLUWA ni mo ti kọ́kọ́ sọ fún Sioni,tí mo sì ròyìn ayọ̀ náà fún Jerusalẹmu.
28. Nígbà tí mo wo ààrin àwọn wọnyi, kò sí olùdámọ̀ràn kan,tí ó lè dá mi lóhùn nígbà tí mo bá ní ìbéèrè.
29. Wò ó! Ìtànjẹ lásán ni gbogbo wọn,òfo ni iṣẹ́ ọwọ́ wọn:Ẹ̀fúùfù lásán ni àwọn ère tí wọ́n gbẹ́.”