Aisaya 3:7-11 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ní ọjọ́ náà, ẹni tí wọn sọ pé kí ó jẹ olórí yóo kígbe pé,“Èmi kò ní jẹ oyè alátùn-únṣe.N kò ní oúnjẹ nílébẹ́ẹ̀ ni kò sí aṣọ.Ẹ má fi mí ṣe olórí yín.”

8. Nítorí Jerusalẹmu ti kọsẹ̀,Juda sì ti ṣubú.Nítorí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ati ìṣe wọn lòdì sí OLUWA,wọ́n ń tàpá sí ògo wíwà rẹ̀.

9. Ìwà àgàbàgebè wọn ń takò wọ́n;wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bíi ti Sodomu:Wọn kò fi bò rárá.Ègbé ni fún wọn,nítorí pé àwọn ni wọ́n mú ibi wá sórí ara wọn.

10. Sọ fún àwọn olódodo pé yóo dára fún wọnnítorí wọn yóo jèrè iṣẹ́ wọn.

11. Ègbé ni fún àwọn eniyan burúkú,kò ní dára fún wọn.Nítorí wọn óo jèrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn.

Aisaya 3