Aisaya 29:10-14 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Nítorí OLUWA ti fi ẹ̀mí oorun àsùnwọra si yín láraÓ ti di ẹ̀yin wolii lójú;ó ti bo orí ẹ̀yin aríran.

11. Gbogbo ìran yìí sì ru yín lójú,bí ọ̀rọ̀ inú ìwé tí a fi èdìdì dì.Nígbà tí wọ́n gbé e fún ọ̀mọ̀wétí wọ́n ní, “Jọ̀wọ́ bá wa kà á.”Ó ní òun kò lè kà ánítorí pé wọ́n ti fi èdìdì dì í.

12. Nígbà tí wọ́n gbé e fún ẹni tí kò mọ̀wétí wọ́n ní, “Jọ̀wọ́ bá wa kà á.”Ó ní òun kò mọ̀wé kà.

13. OLUWA ní,“Nítorí pé ẹnu nìkan ni àwọn eniyan wọnyi fi ń súnmọ́ mi,ètè lásán ni wọ́n sì fi ń yìn mí;ṣugbọn ọkàn wọn jìnnà sí mi.Òfin eniyan, tí wọn kọ́ sórí lásán, ni ìbẹ̀rù mi sì jẹ́ fún wọn.

14. Nítorí náà n óo tún ṣe ohun ìyanu sí àwọn eniyan wọnyi,ohun ìyanu tí ó jọni lójú.Ọgbọ́n yóo parẹ́ mọ́ àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n ninu,ìmọ̀ràn yóo sì parẹ́ mọ́ àwọn ọ̀mọ̀ràn níkùn.”

Aisaya 29