Aisaya 23:16-18 BIBELI MIMỌ (BM)

16. “Mú hapu, kí o máa káàkiri ààrin ìlú,ìwọ aṣẹ́wó, ẹni ìgbàgbé.Máa kọ orin dídùn ní oríṣìíríṣìí,kí á lè ranti rẹ.”

17. Nígbà tí aadọrin ọdún bá pé, OLUWA yóo ranti Tire. Yóo pada sídìí òwò aṣẹ́wó rẹ̀, yóo sì máa bá gbogbo ìjọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ṣe òwò àgbèrè.

18. Yóo ya ọjà tí ó ń tà ati èrè tí ó bá jẹ sọ́tọ̀ fún OLUWA, kò ní máa to èrè rẹ̀ jọ, tabi kí ó máa kó o pamọ́; ṣugbọn yóo máa lò wọ́n láti pèsè oúnjẹ ati aṣọ fún àwọn tí ó bá ń sin OLUWA.

Aisaya 23