Aisaya 21:3-6 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Nítorí náà, gbogbo ẹ̀gbẹ́ ní ń dùn mí,gbogbo ara ní ń ro míbí obinrin tí ń rọbí lọ́wọ́.A tẹrí mi ba kí n má baà gbọ́ nǹkankan,wọ́n dẹ́rù bà mí kí n má baà ríran.

4. Ọkàn mi dààmú, jìnnìjìnnì dà bò mí;wọ́n ti sọ àfẹ̀mọ́júmọ́ tí mò ń retí di ìbẹ̀rù mọ́ mi lọ́wọ́.

5. Wọ́n tẹ́ tabili, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sílẹ̀wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu.Ariwo bá ta pé“Ẹ gbéra nílẹ̀, ẹ̀yin ológun!Ẹ fepo pa asà yín.”

6. Nítorí OLUWA wí fún mi pé:“Lọ fi aṣọ́nà ṣọ́ ojú ọ̀nà,kí ó máa kéde ohun tí ó bá rí.

Aisaya 21