Aisaya 10:3-5 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Kí ni ẹ óo ṣe lọ́jọ́ ìjìyà yíntí ìparun bá dé láti òkèèrè?Ta ni ẹ óo sá tọ̀ lọ fún ìrànlọ́wọ́?Níbo ni ẹ óo kó ọrọ̀ yín sí?

4. Kò sí ohun tí ó kù àfi kí ẹ kú lójú ogun,tabi kí ẹ ká góńgó láàrin àwọn tí wọ́n kó lẹ́rú.Sibẹsibẹ inú OLUWA kò ní rọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò ní dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.

5. Háà! Asiria!Orílẹ̀-èdè tí mò ń lò bíi kùmọ̀, ati bíi ọ̀pánígbà tí inú bá bí mi.

Aisaya 10