19. Mo sì sọ fún ańgẹ́lì tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?”Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Júdà, Ísírélì, àti Jérúsálẹ́mù ká.”
20. Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
21. Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?”O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Júdà ká, tóbẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sòkè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orilẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sorí ilẹ̀ Júdà láti tú enìyàn rẹ̀ ká.”