1. Ní osù kẹ́jọ ọdún kejì Ọba Dáríúsì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekaráyà ọmọ Bérékáyà, ọmọ Ídò wòlíì pé:
2. “Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
3. Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn: Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí Ọ̀dọ̀ mi,’ Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4. Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé: Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ ogun wí: ‘Ẹ yípadà nísinsìnyìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.