Sefanáyà 1:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. “Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Júdààti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jérúsálẹ́mù.Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Báálì, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣàpẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,

5. àti àwọn tí wọn ń foríbalẹ̀ tí wọnń sin ogun ọ̀run lórí òrùlé.Àwọn tí wọn ń sìn, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,tí wọ́n sì ń fi Mólékì búra.

6. Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.

7. Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run,nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀. Olúwa ti pèṣè ẹbọ kan sílẹ̀,ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.

8. Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa,Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọnọmọ ọba ọkùnrin,pẹ̀lú gbogboàwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.

Sefanáyà 1