Sáàmù 86:8-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Nínú àwọn òrìṣà kò sì ẹni tí ó dà bí Rẹ, Olúwa:kò sí àwọn iṣẹ́ tí a le fi wé tìrẹ.

9. Gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè tí ìwọ dáyóò wá, láti wá jọ́sìn níwájú Rẹ, Olúwa;wọn o mú ògo wà fún orúkọ Rẹ̀.

10. Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ si ń ṣe ohun ìyanu;ìwọ nìkan ní Ọlọ́run.

11. Kọ́ mi ní ọ̀nà Rẹ, Olúwa,èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ Rẹ;fún mi ní ọkàn tí kì í yapa,kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ Rẹ.

12. Èmi o yìn ọ, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkan mi;èmi o fògo fún orúkọ Rẹ títí láé

13. Nítorí títóbi ní ìfẹ́ Rẹ̀ si mi;ìwọ ti gba mí kúrò nínú ọ̀gbun ìsà okú.

14. Àwọn onígbéraga ń dojú kọ mí, Ọlọ́run;àti ìjọ̀ àwọn alágbára ń wáọkàn mi kiri,wọn kò sì fi ọ pè.

Sáàmù 86