Sáàmù 86:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dà mí lóhùn,nítorí mo jẹ́ talákà àti aláìní.

2. Dáàbòbò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ:ìwọ ní Ọlọ́run mi,gbà ìránṣẹ́ Rẹ làtí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.

3. Ṣàánú fún mi, Olúwa,nítorí èmi ń pe ọ́ ní gbogbo ọjọ́.

4. Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ Rẹ,nítorí ìwọ, Olúwa,ní mo gbé ọkan mí sókè sí.

5. Ìwọ ń daríjì, ìwọ sì dára, Olúwa,ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn ti ń ké pè ọ́,

6. Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa;tẹ́tí sí ẹkún fún àánú.

7. Ní ọjọ́ ipọ́njú mi èmi yóò pe ọ́,nítorí ìwọ yóò dá mí lóhùn.

8. Nínú àwọn òrìṣà kò sì ẹni tí ó dà bí Rẹ, Olúwa:kò sí àwọn iṣẹ́ tí a le fi wé tìrẹ.

9. Gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè tí ìwọ dáyóò wá, láti wá jọ́sìn níwájú Rẹ, Olúwa;wọn o mú ògo wà fún orúkọ Rẹ̀.

Sáàmù 86