3. Wọ́n tú ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omiyí Jérúsálẹ́mù ká,kò sì sí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
4. Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí o yí wa ká,àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wá ká.
5. Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ o máa bínú títí láé?Yóò ti pẹ́ tó ti òwú Rẹ̀ yóò ha jò bi iná?
6. Tú ìbínú Rẹ̀ jáde sí orílẹ̀-èdètí kò ní ìmọ̀ Rẹ,lórí àwọn ìjọbatí kò pe orúkọ Rẹ;
7. Nítorí wọ́n ti run Jákọ́bùwọ́n sì sọ ibùgbé Rẹ̀ di ahoro
8. Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùnjẹ́ kí àánú Rẹ yà kánkán láti bá wa,nítorí ti a Rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.