Sáàmù 76:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní Júdà ni a mọ Ọlọ́run;orúkọ Rẹ̀ sì lágbára ní Ísírẹ́lì

2. Àgọ́ Rẹ̀ wà ní Sálẹ́mù,ibùgbé Rẹ̀ ní Síónì.

3. Níbẹ̀ ní o ṣẹ́ ọfà,asà àti àwọn idà, ohun ìjà ogun. Sela

4. Iwọ ni ògo àti ọláJu òkè-ńlá íkogun wọ̀nyìí lọ.

5. Àwọn akíkanjú ọkùnrin A kó àwọn akíkanjú ogun ní ìkógunwọn sún oorun ìgbẹ̀yìn wọn;kò sí ọ̀kan nínú àwọn ajaguntó lè gbé ọwọ́ Rẹ̀ sókè.

6. Ní ìfìbú Rẹ, Ọlọ́run Jákọ́bù,àwọn ẹsin àti kẹ̀kẹ́ ogun sì dúbúlẹ̀ ṣíbẹ̀.

Sáàmù 76