Sáàmù 75:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Nígbà tí ayé àti àwọn ènìyàn ibẹ̀ wárìrì,Èmi ni mo di òpó Rẹ̀ mú ṣinṣin.

4. Èmí wí fún àwọn agbéraga péẸ má ṣe gbéraga mọ́;àti sí ènìyàn búburú;Ẹ má ṣe gbé ìwo yín sókè.

5. Ẹ máa ṣe gbe ìwo yín sókè sí ọ̀run;ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọrùn líle.”

6. Nítorí ìgbẹ́kẹ̀lé kò ti ìlà-oòrùn wátàbí ní ìwọ̀-oòrùn,bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe láti gúsù wá.

7. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni olùdajọ́;Òun Rẹ̀ ẹnìkan sílẹ̀, ó sí ń gbé ẹlòmíràn ga.

8. Ní ọwọ́ Olúwa ni ago kan wà,ọtí wáìnì náà sì pọ́n,ó kún fún àdàlú, ó fún ọtí àdàlú tí a pòpọ̀ mọ́ òórùn dídùntí ó tú jáde, àti búburú ayé gbogbomú u sílẹ̀ pátapáta.

9. Ṣùgbọ́n èmi, ó máa ròyìn Rẹ títí láé;Èmi ó kọrin ìyìn sí Ọlọ́run Jákọ́bù (Ísírẹ́lì)

Sáàmù 75