Sáàmù 74:8-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Wọ́n wí ní ọkàn wọn. “Àwa ó run wọ́n pátapáta!”Wọ́n sun gbogbo ibi ìjọ́sìn Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà.

9. A kò fún wa ní àmì iṣẹ́ ìyanu kankan;kò sí wòlíì kankanẹnìkan kan wa kò mọ ìgbà tí eléyìí yóò dà.

10. Àwọn ọ̀ta yóò ti kùn sí ọ pẹ́ tó, Ọlọ́run?Àwọn ọ̀ta yóò ha ba orúkọ Rẹ jẹ́ títí láé?

11. Èéṣe tí ìwọ fi dá ọwọ́ Rẹ dúró, ọwọ́ ọ̀tún Rẹ?Mú-un kúrò nínú ìṣẹ́po aṣọ Rẹ kí o sì run wọ́n!

12. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run ni ọba mi láti ìgbà pípẹ́;ó mú ìgbàlà wá sórí ilẹ̀ ayé.

13. Ìwọ ni ó la òkun sílẹ̀ nípa agbára Rẹ;Ìwọ fọ́ orí àwọn abàmì ẹ̀dá nínú omi

14. Ìwọ fọ́ orí Lefiatani túútúú, o sì fi se oúnjẹ fun àwọn ẹ̀dá ti ń gbé inú ìjùTìrẹ ní ọ̀sán, tìrẹ sì ni alẹ́ pẹ̀lú;ìwọ fi ìdí òòrùn àti òṣùpá lélẹ̀.

15. Iwọ ya orísun omi àti iṣàn omi;Ìwọ mú kí odò tó ń ṣàn gbẹ

16. Tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ ni òru pẹ̀lú;ìwọ yà oòrùn àti òsùpá.

17. Ìwọ pààlà etí ayé;Ìwọ dá ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti ìgbà òtútù.

Sáàmù 74