Sáàmù 69:8-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi;àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;

9. Nítorí ìtarà ilé Rẹ jẹ mí run,àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.

10. Nígbà tí mo sunkúntí mo sì ń fi ààwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyàèyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;

11. Nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà,àwọn ènìyàn ń pòwe mọ́ mi.

12. Àwọn tí ó jòkòó ní ẹnu ibodè ń bú mi,mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.

Sáàmù 69