Sáàmù 69:25-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Kí ibùjókòó wọn di ahoro;kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.

26. Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù,àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe

27. Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn;Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà Rẹ.

28. Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyèkí á má kà wọn pẹ̀lú àwọn olódodo.

29. Ṣùgbọ́n talákà àti ẹni-ìkáánú ni èmí,Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà Rẹ gbé mi lékè.

Sáàmù 69