Sáàmù 66:12-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ìwọ mú àwọn ènìyàn gun wá ní oríàwa la iná àti omi kọjáṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.

13. Èmi ó wá sí tẹ́ḿpìlì Rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísunkí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ

14. Ẹ̀jẹ́ ti ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọnígbà tí mo wà nínú ìsòro.

15. Èmi o sun ẹbọ ọlọ́ràá sí ọàti ẹbọ ọ̀rá àgbò;èmi o rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. Sela

16. Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa;ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.

17. Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i:Ìyìn Rẹ̀ wà ní ẹnu mi.

18. Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;

19. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́o ti gbọ́ ohun mi nínú àdúrà.

20. Ìyìn ni fún Ọlọ́runẹni tí kò kọ àdúrà mitàbí mú ìfẹ́ Rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!

Sáàmù 66