Sáàmù 5:8-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo Rẹ,nítorí àwọn ọ̀ta mi,mú ọ̀nà Rẹ tọ́ níwájú mi.

9. Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́;ọkàn wọn kún fún ìparun.ọ̀nà ọ̀fun wọn ni iṣà òkú tí ó sí sílẹ̀;pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.

10. Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run!Jẹ́ kí rìkísí wọn jẹ́ ìṣubú wọn.Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn,nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.

11. Ṣùgbọ́n jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀;jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí.Tan ààbò Rẹ sórí wọn,àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ Rẹ yóò máa yọ̀ nínú Rẹ.

12. Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo;ìwọ fi ojú rere Rẹ yí wọn ká bí àṣà.

Sáàmù 5