Sáàmù 39:2-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Mo fi ìdákẹ́ ya odi;mo tilẹ̀ pa ẹnu mi mọ́kúrò nínú ọ̀rọ̀ rere;ìbànújẹ́ mi sì pọ̀ síi.

3. Àyà mi gbóná ní inú mi,nígbà tí mo ń ṣàṣàrò,ina ràn;nígbà náà ni mo fi ahọ́n mi sọ̀rọ̀.

4. Olúwa,jẹ́ kí èmi kí ó mọ òpin mi,àti ìwọ̀n ọjọ́ mi, bí ó ti ríkí èmi kí o le mọ ìgbà tí mó ní níhìn-ín.

5. Ìwọ ti ṣe ayé mibí ìbú àtẹ́lẹwọ́,ọjọ́ orí mi sì dàbí asánní iwájú Rẹ:Dájúdájú olúkúlùkù ènìyàn nínúìjókòó rere Rẹ̀ jásí asán pátapáta. Sela

6. Nítòótọ́ ni olúkúlùkù ń rìn kiri bí òjìji.Nítòótọ́ ni wọ́n ń yọ ara wọn lẹ́nu lórí asán;wọ́n ń kó ọrọ̀ jọ,wọn kò sì mọ ẹni tí yóò ko lọ.

7. Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, Olúwa,kín ni mo ń dúró dè?Ìrètí mí ń bẹ ní ọ̀dọ̀ Rẹ.

Sáàmù 39