Sáàmù 37:16-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ohun díẹ̀ tí olódodo nísàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú.

17. Nítorí pé a ó ṣẹ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18. Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn adúró ṣinṣin,àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;

19. Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.

20. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé,àwọn ọ̀ta Olúwa yóò dà bíẹwà oko tútù;wọn fò lọ;bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.

21. Àwọn ènìyàn búburú yá,wọn kò sì san-án padà,ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa fi fún ni;

Sáàmù 37