Sáàmù 37:15-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.

16. Ohun díẹ̀ tí olódodo nísàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú.

17. Nítorí pé a ó ṣẹ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18. Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn adúró ṣinṣin,àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;

19. Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.

20. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé,àwọn ọ̀ta Olúwa yóò dà bíẹwà oko tútù;wọn fò lọ;bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.

21. Àwọn ènìyàn búburú yá,wọn kò sì san-án padà,ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa fi fún ni;

22. Nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkúnni yóò jogún ilẹ̀ náà,àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.

23. Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wáláti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,o si ṣe inú dídùn sí ọ̀nà Rẹ̀;

24. Bí ó tilẹ̀ ṣubúa kì yóò ta á nù pátapáta,nítorí tí Olúwa di ọwọ́ Rẹ̀ mú.

25. Èmi ti wà ni èwe,báyìí èmí sì dàgbà;ṣíbẹ̀ èmi kò ì tíi rí kia kọ olódodo ṣílẹ̀,tàbí kí irú ọmọ Rẹ̀máa ṣagbe oúnjẹ.

26. Aláàánú ni òun nígbà gbogboa máa yá ni;a sì máa bùsí i fún ni.

27. Lọ kúrò nínú ibi,kí o sì máa ṣe rere;nígbà náà ni ìwọ gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.

Sáàmù 37