Sáàmù 33:11-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé,àní ìrò inú Rẹ̀ láti ìrandíran ni.

12. Ìbùkún ni fún orílẹ̀ èdè náà Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀,àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní Rẹ̀.

13. Olúwa wò láti ọ̀run wá;Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.

14. Níbi tí ó ti jókòó lóríi ìtẹ́Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé

15. ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà,ó sì kíyèsí ìṣe wọn.

Sáàmù 33