Sáàmù 135:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ẹni tí ó rán àmì àti iṣẹ ìyanu sí àrin Rẹ̀,ìwọ Éjíbítì, sí ara Fáráò,àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ Rẹ̀ gbogbo.

10. Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀ èdè púpọ̀,tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.

11. Síónì, ọba àwọn ará Ámorì, àti Ógù,ọba Báṣánì, àti gbogbo ìjọba Kénánì:

12. Ó sì fi ilẹ̀ wọn fúnni ní ìní,ìní fún Ísírẹ́lì, ènìyàn Rẹ̀.

13. Olúwa orúkọ Rẹ dúró láéláé;ìrántí Rẹ Olúwa, láti ìran-díran.

14. Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn Rẹ̀,yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Rẹ̀.

15. Sílífà Òun wúrà ní èrè àwọn aláìkọlà,iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn.

Sáàmù 135