Sáàmù 135:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa,nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.

3. Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun;ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ Rẹ̀; ní torí tí ó dùn.

4. Nítorí tí Olúwa ti yàn Jákọ́bù fún ara Rẹ̀;àní Ísírẹ́lì fún ìṣúra ààyò Rẹ̀.

5. Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi,àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.

6. Ohunkóhun tí ó wu Olúwa, Òun ní iṣe ní ọ̀run,àti ní ayé, ní òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.

Sáàmù 135