Sáàmù 119:7-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣinbí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo Rẹ̀.

8. Èmi yóò gbọ́ràn sí asẹ Rẹ̀:Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátapáta.

9. Báwo ni àwọn èwe ènìyàn yóò ti ṣe pa ọ̀nà Rẹ̀ mọ́?Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ Rẹ.

10. Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mimá ṣe jẹ́ kí èmi yàpa kúrò nínú àṣẹ̀ Rẹ.

11. Èmi ti pa ọ̀rọ̀ Rẹ mọ́ ní ọkàn mikí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ

12. Ìyìn ni fún Olúwa;kọ́ mi ní àsẹ Rẹ.

13. Pẹ̀lú ètè mi èmi tún sírògbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu Rẹ.

14. Èmi yọ̀ nínú títẹ̀lé òrin Rẹbí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọlá ńlá.

15. Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà Rẹèmi sì kíyèsí ọ̀nà Rẹ

16. Inú mi dùn sí àṣẹ Rẹ;èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà Rẹ.

Sáàmù 119