Sáàmù 119:18-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. La ojú mi kí èmi lè ríran ríohun ìyanu tí ó wà nínú òfin Rẹ.

19. Àlejò ní èmi jẹ́ láyé;Má ṣe pa àṣẹ Rẹ mọ́ fún mi.

20. Ọkàn mi pòrúúru pẹ̀lú ìfojúsọ́nànítorí òfin Rẹ nígbà gbogbo.

21. Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn-úntí ó sìnà kúrò nínú àṣẹ Rẹ.

22. Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi,nítorí èmi pa òfin Rẹ mọ́.

Sáàmù 119