Sáàmù 119:114-121 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

114. Ìwọ ni ààbò mi àti aṣà mi;èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ Rẹ.

115. Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú,kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!

116. Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Rẹ,kí èmi kí ó lè yèMá sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.

117. Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu;nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin Rẹ.

118. Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó sìnà kúrò nínú òfin Rẹ,nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.

119. Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọyọ kúrò bí i ìdàrọ́;nítorí náà, èmi fẹ́ òfin ẹ̀.

120. Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí Rẹ̀:èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin Rẹ

121. Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́:má ṣe fi mi sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.

Sáàmù 119