Sáàmù 118:20-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwaibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.

21. Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dámi lóhùn;ìwọ sì di ìgbàlà mi.

22. Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀ sílẹ̀ni ó di pàtàkì òkúta igun ilé;

23. Olúwa ti ṣe èyíó ṣe ìyanu ní ojú wa.

24. Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá:ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú Rẹ̀.

25. Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.

26. Ìbùkún ni fún àwọn tí ó wá ní orúkọ Olúwa.Láti ilé Olúwa wá ní àwa fi ìbùkún fún ọ.

Sáàmù 118