Sáàmù 118:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ìwọ tì mi gidigidi kí ń lè subú,ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.

14. Olúwa ni agbára àti orin mi;ó si di ìgbàlà mi.

15. Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo:“ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!

16. Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbé ga;ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”

17. Èmi kì yóò kú ṣùgbọ́n èmi yóò yè,èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.

18. Olúwa bá mi wí gidigidi,ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.

Sáàmù 118