Sáàmù 106:41-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

41. Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀ èdè lọ́wọ́,àwọn ọ̀tá wọn sì jọba lórí wọn.

42. Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọ́n lójúwọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.

43. Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n,Ṣíbẹ̀ wọ́n si ń ṣọ̀tẹ̀ sí ìwọ́n sì sòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

44. Ṣùgbọ́n o kíyèsí wọn nítorí ìṣòronígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn;

45. Ó rántí májẹ̀mú Rẹ̀ nítorí wọnNítorí agbára ìfẹ́ Rẹ̀, ó ṣàánú wọn.

46. Lójú gbogbo àwọn tí o kó wọn ní ìgbèkùnó mú wọn rí àánú.

Sáàmù 106