Sáàmù 103:16-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Afẹ́fẹ́ fẹ́ kọjá lọ lórí Rẹ̀,kò sì rántí ibùjókòó Rẹ̀ mọ́.

17. Ṣùgbọ́n láti ayé rayé ni ìfẹ́ Olúwa ti wà pẹ̀lú àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ̀,àti òdodo Rẹ̀ wà láti ọmọ dé ọmọ

18. Sí àwọn tí ó pa májẹ̀mú Rẹ̀ mọ́àti àwọn tí ó rántí òfin Rẹ̀ láti ṣe wọ́n.

19. Olúwa ti pèsè ìtẹ́ Rẹ̀ nínú ọ̀run,ìjọba Rẹ̀ ní ó sì borí ohun gbogbo.

20. Yin Olúwa, ẹ̀yin ańgẹ́lì Rẹ̀ tí ó ní ipá,tí ó pa òfin ọ̀rọ̀ Rẹ̀ mọ́

21. Yin Olúwa, ẹ̀yin ogun ọ̀run Rẹ̀ gbogbo,ẹ̀yin ìránṣẹ́ Rẹ̀ tí ń ṣe ìfẹ́ Rẹ̀.

22. Yin Olúwa, gbogbo iṣẹ́ Rẹ̀ níibi gbogbo ìjọba Rẹ̀.Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Sáàmù 103