Róòmù 6:10-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Kírísítì kú lẹ́ẹ̀kan soso, láti sẹ́gun agbára ẹ̀ṣẹ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó wà láàyè títí ayé àìnípẹ̀kun ní ìdàpọ̀ mímọ́ pẹ̀lú Ọlọ́run.

11. Nítorí náà, ẹ máa wo ògbólógbòó ara ẹ̀ṣẹ̀ yín gẹ́gẹ́ bí òkú tí kò ní ohunkóhun í ṣe pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ mọ́. Dípò èyí, máa gbé ìgbé ayé yín fún Ọlọ́run nìkan ṣoṣo. Ẹ dúró gbọn-in gbọn-in fún un, nípasẹ̀ Jésù Kírísítì Olúwa wa.

12. Nítorí náà kí ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀sẹ̀ jọba lórí ara kíkú yín kí ó lè ba à máa ṣe ìfẹ́kùfẹ̀ẹ̀ rẹ̀.

13. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀yà ara yín kan di ohun èlò ìkà, nípa ẹ̀ṣẹ̀ dídá. Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ǹda wọn fún Ọlọ́run pátápátá. Wọ́n ti di ààyè, ẹ jẹ́ kí wọn di ohun èlò ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí ó lè lò wọ́n fún àwọn ìlànà rẹ̀ tí ó dára.

14. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ kì yóò tún ní ipá lórí yín mọ́, nítorí ẹ̀yin kò sí lábẹ́ ìdè òfin, bí kò ṣe lábẹ́ oore-ọ̀fẹ́.

15. Ǹjẹ́ èyí túmọ̀ sí pé, nísinsinyìí, a lè tẹ̀ṣíwájú láti máa dẹ́ṣẹ̀ láì bìkítà? (Nítorí ìgbàlà wa kò dúró nípa òfin mọ́, bí kò ṣe nípa gbígba oore ọ̀fẹ́ Ọlọ́run)

Róòmù 6